2. Èmi yóò sì fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò sì sọ ọ́ di púpọ̀ gidigidi.”
3. Ábúrámù sì dojúbolẹ̀, Ọlọ́run sì wí fún un pé.
4. “Ní ti èmi, májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ nìyí. Ìwọ yóò di baba orílẹ̀ èdè púpọ̀.
5. A kì yóò pe orúkọ rẹ̀ ní Ábúrámù mọ́, bí kò ṣe Ábúráhámù, nítorí, mo ti sọ ọ́ di baba orílẹ̀ èdè púpọ̀.
6. Èmi yóò mú ọ bí si lọ́pọ̀lọ́pọ̀, ọ̀pọ̀ orílẹ̀ èdè ni èmi yóò sì mú ti ara rẹ jáde wá, àwọn ọba pẹ̀lú yóò sì ti inú rẹ jáde.
7. Èmi yóò sì gbé májẹ̀mú mi kalẹ̀ láàrin èmi àti ìwọ, ní májẹ̀mú ayérayé àti láàrin irú ọmọ rẹ ní ìran-ìran wọn, láti máa ṣe Ọlọ́run rẹ àti ti irú ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ.
8. Gbogbo ilẹ̀ Kénánì níbi tí ìwọ ti ṣe àjèjì ni èmi yóò fi fún ọ àti ìran rẹ lẹ́yìn rẹ láéláé, Èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.”
9. Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Ábúráhámù pé, “Ìwọ máa pa májẹ̀mú mí mọ́, ìwọ àti irú ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ àti àwọn ìran tí ó ń bọ̀.
10. Èyí ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ àti ìran rẹ lẹ́yìn rẹ, májẹ̀mú tí ẹ gbọdọ̀ pa mọ́. Gbogbo ọkùnrin yín ni a gbọdọ̀ kọ ní ilà.
11. Ẹ̀yin yóò kọ ara yín ní ilà, èyí ni yóò jẹ́ àmì májẹ̀mú láàrin wa.
12. Ní gbogbo ìran tí ń bọ̀ lẹ̀yìn, gbogbo ọkùnrin ni a gbọdọ̀ kọ ni ilà ní ọjọ́ kẹjọ tí a bí wọn, àti àwọn tí a bí ní ilé rẹ, tàbí tí a fi owó rà lọ́wọ́ àwọn àjèjì, àwọn tí kì í ṣe ọmọ rẹ̀. Èyí yóò sì jẹ́ májẹ̀mú láéláé tí yóò wà láàrin Èmi àti irú ọmọ rẹ.
13. Ìbá à ṣe ẹni tí a bí nínú ilé rẹ, tàbí ẹni tí fi owó rà, gbọdọ̀ kọ wọ́n ní ilà; májẹ̀mú mí lára yín yóò jẹ́ májẹ̀mú ayérayé.
14. Gbogbo ọmọkùnrin tí kò bá kọ ilà, tí a ko kọ ní ilà abẹ́, ni a ó gé kúrò láàrin àwọn ènìyàn rẹ̀, nítorí pé ó da májẹ̀mú mi”