Ísíkẹ́lì 48:5-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. “Éfúráímù yóò ní ìpín kan; èyí yóò jẹ́ ààlà agbégbé Mánásè láti ìlà oòrùn lọ sí ìwọ oòrùn.

6. “Rúbẹ́nì yóò ní ìpín kan; èyí yóò jẹ́ ààlà agbégbé Éfúráímù láti ìlà oòrùn títí dé ìwọ̀ oòrùn.

7. “Júdà yóò ní ìpín kan; èyí yóò jẹ́ ààlà agbégbé Rúbẹ́nì láti ìlà oòrùn lọ sí ìwọ̀ oòrùn.

8. “Ààlà agbégbé Júdà láti ìlà oòrùn dé ìwọ̀ oòrùn yóò jẹ́ ìpín tí ìwọ yóò gbé kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn pàtàkì. Yóò jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n ìgbọ̀nwọ́ (25,000) ní fífẹ̀, gígùn rẹ̀ láti ìlà oòrùn lọ sí ìwọ̀ oòrùn yóò jẹ́ bákan náà pẹ̀lú àwọn ìpín ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan; ilé mímọ́ yóò wà ní àárin gbùngbùn rẹ̀.

Ísíkẹ́lì 48