Ísíkẹ́lì 37:10-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Nítorí náà, mo ṣọtẹ́lẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ṣe pa á láṣẹ fún mi, èémí sì wọ inú wọn; Wọ́n di alààyè, wọ́n sì dìde dúró lórí ẹṣẹ̀ wọn—pẹ̀lú ìhámọ́ra tí ó pọ̀.

11. Lẹ́yìn náà ó ṣọ fún mi: “Ọmọ ènìyàn, àwọn egungun wọ̀nyí ni gbogbo ìdílé Ísírẹ́lì. Wọ́n ṣọ wí pé, ‘Egungun wa ti gbẹ ìrètí wa sì ti lọ; a ti gé wa kúrò.’

12. Nítorí náà ṣọtẹ́lẹ̀, kí o sì ṣọ fun wọn pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: Ẹ̀yin ènìyàn mi, Èmi yóò sí àwọn ibojì yín, èmi yóò sì mú yín wá si ilẹ̀ Isírẹ́lì.

13. Ẹ̀yin o sì mọ̀ èmi ni Olúwa, nígbà tí èmi bá ti sí bojì yín, ẹ̀yin ènìyàn mi, ti èmi bá si mú un yín dìde kúrò nińú bojì yín

Ísíkẹ́lì 37