Ísíkẹ́lì 30:1-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá: wí pé:

2. “Ọmọ ènìyàn, ṣọtẹ́lẹ̀ kí o sì wí pé: ‘Báyìí ní Olúwa Ọlọ́run wí:“ ‘Pohùnréré ẹkún kí o sì wí pé,“Ó ṣe fún ọjọ́ náà!”

3. Nítorí ọjọ́ náà sún mọ́ tòsíàní ọjọ́ Olúwa sún mọ́ tòsíỌjọ́ tí ọjọ́ ìkùukùu ṣú dúdú,àsìkò ìparun fún àwọn aláìkọlà

4. Idà yóò wá sórí Éjíbítììrora ńlá yóò sì wá sórí KúṣìNígbà tí àwọn tí a pa yóò subú ní Éjíbítìwọn yóò kò ọrọ̀ rẹ̀ lọìpìlẹ̀ rẹ̀ yóò sì wó lulẹ̀.

5. Kúṣì àti Pútì, Lídíà àti gbogbo Árábù, Líbíyà àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ ìlérí yóò ṣubú nípa idà papọ̀ pẹ̀lú Éjíbítì.

6. “ ‘Èyí yìí ní Olúwa wí:“ ‘Àwọn alejò Éjíbítì yóò ṣubúagbára ìgbéraga rẹ yóò kùnàláti Mígídólì títí dé Ásúwánìwọn yóò ti ipa idà ṣubú láàárin rẹ;ní Olúwa Ọlọ́run wí:

7. Wọn yóò sì wàlára àwọn ilẹ̀ tí ó di ahoro,ìlú rẹ yóò sì wàní ara àwọn ìlú tí ó di ahoro.

8. Lẹ́yìn náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa,nígbà tí mo bá gbé iná kalẹ̀ ní Ijíbítìtí gbogbo àwọn olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ bá parun.

9. “ ‘Ní ọjọ́ náà oníṣẹ́ yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde nínú ọkọ̀ ojú omi láti dẹ́rùbà Kúsì kúrò nínú ìtẹ́lọ́rùn rẹ̀. Ìrora yóò wá sórí wọn gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ ìparun Éjíbítì: Kíyèsí i, ó dé.

Ísíkẹ́lì 30