Ísíkẹ́lì 11:2-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin yìí ló ń pète ibi, wọ́n sì ń gba ìmọ̀ràn búburú kalẹ̀ nínú ìlú.

3. Wọ́n ní, ‘kò ha tí ì tó àsìkò láti kọ́lé? Ìlú yìí ni ìkòkò ìdáná, àwa sì ni ẹran’.

4. Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀ nípa wọn; ọmọ ènìyàn, sọ tẹ́lẹ̀.”

5. Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé mi, ó sì wí pé, “Sọ̀rọ̀!” Báyìí ni Olúwa wí, Ohun tí ẹ-ń sọ níyìí, ilé Ísírẹ́lì, mo mọ ohun tó wà lọ́kàn yín.

6. Bí ẹ ṣe ń pànìyàn tún ti pọ̀ síi nínú ìlú, òkú sì ti kún gbogbo ojú pópó.

7. “Torí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run wí, àwọn òkú tí ẹ pa sáàrin yín ni ẹran, ìlú yìí sì ni ìkòkò ìdáná ṣùgbọ́n n ó le yín jáde níbẹ̀.

8. Ẹ bẹ̀rù idà, n ó sì mú idà wá sórí yín, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.

Ísíkẹ́lì 11