Ísíkẹ́lì 10:4-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ògo Olúwa sì kúrò lórí àwọn kérúbù, ó bọ́ sí ibi ìloro tẹ́ḿpìlì. Ìkùukùu sì bo inú tẹ́ḿpìlì, àgbàlá sì kún fún ìmọ́lẹ̀ àti ògo Olúwa.

5. A sì gbọ́ ariwo ìyẹ́ àwọn kérúbù yìí títí dé àgbàlá tó wà níta gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí Ọlọ́run Olódùmáre bá ń sọ̀rọ̀.

6. Nígbà tí Olúwa pàṣẹ fún ọkùnrin aláṣọ funfun yìí pé, “Mú iná láàrin àwọn kẹ̀kẹ́, láàrin àwọn kérúbù,” ó sì lọ dúró sẹ́gbẹ̀ẹ́ àwọn kẹ̀kẹ́ náà.

7. Ọ̀kan nínú àwọn kérúbù sì nawọ́ síbi iná tó wà láàrin kérúbù yóòkù. Ó mú lára rẹ, ó fi sínú ọwọ́ ọkùnrin aláṣọ funfun, òun náà gbàá, ó sì jáde lọ.

8. (Ohun tó dàbí ọwọ́ ènìyàn wà lábẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù yìí).

9. Mo sì rí i pé kẹ̀kẹ́ mẹ́rin wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ àwọn kérúbù yìí, kẹ̀kẹ́ kọ̀ọ̀kan wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ kérúbù kọ̀ọ̀kan; àwọn kẹ̀kẹ́ yìí ń tàn yanran bí àpapọ̀ àwọ̀ ewéko àti pupa rẹ́súrẹ́sú.

10. Ní ti ìrísí wọn, gbogbo wọn jọra wọn; ọ̀kọ̀ọ̀kan rí bí ìgbà tí kẹ̀kẹ́ kan wà nínú kẹ̀kẹ́ mìíràn.

11. Nígbà tí wọ́n ń lọ, wọ́n tẹ̀lé ọ̀kan nínú ọ̀nà mẹ́rin tí àwọn kérúbù dojú kọ; àwọn kẹ̀kẹ́ náà kò yípadà bí àwọn kérúbù ti ń lọ. Àwọn kérúbù ń lọ síbi tí orí dojú kọ láì yà.

12. Gbogbo ara wọn àti ẹ̀yìn, ọwọ́ àti ìyẹ́ wọn àwọn kẹ̀kẹ́ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọn ló ní ojú tó yí wọn ká.

Ísíkẹ́lì 10