5. ‘Èyí ni ohun tí Èmi fi bá a yín dá májẹ̀mú nígbà tí ẹ jáde kúrò ní Éjíbítì, bẹ́ẹ̀ ni Ẹ̀mí ì mi sì wà pẹ̀lú yín. Ẹ má ṣe bẹ̀rù.’
6. “Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Láìpẹ́ jọjọ, Èmi yóò mi àwọn ọrun àti ayé, òkun àti ìyàngbẹ ilẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i.
7. Èmi yóò mi gbogbo orílẹ̀ èdè, ìfẹ́ gbogbo orílẹ̀ èdè yóò fà sí Tẹ́ḿpìlì yìí, Èmi yóò sì kùn ilé yìí pẹ̀lu ògo;’ ni Olúwa àwọn ọmọ ogun wí.
8. ‘Tèmi ni fàdákà àti wúrà,’ ni Olúwa àwọn ọmọ ogun wí.
9. ‘Ògo ìkẹyìn àwọn ọmọ-ogun ilé yìí yóò pọ̀ ju ti ìṣáájú lọ;’ ni Olúwa àwọn ọmọ ogun wí: ‘Àti ní ìhín yìí ni Èmi ó sì fi àlàáfíà fún ni’, ni Olúwa àwọn ọmọ ogun wí.”
10. Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹsàn-án ní ọdún kejì Dáríúsì, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Hágáì wá pé:
11. “Báyìí ni Olúwa alágbára wí: ‘Béèrè lọ́wọ́ àwọn àlùfáà ohun tí òfin wí pé: