17. bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gòkè lọ sì Jerúsálémù tọ àwọn tí í ṣe Àpósítélì ṣáájú mi: ṣùgbọ́n mo lọ sí Árábíà, mo sì tún padà wá sí Dámásíkù.
18. Lẹ́yìn ọdún mẹ́ta, nígbà náà ni mo gòkè lọ sì Jerúsálémù láti lọ kì Pétérù, mo sì gbé ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní ìjọ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún,
19. Èmi kò ri ẹlòmíràn nínú àwọn tí ó jẹ́ Àpósítélì, bí kò ṣe Jákọ́bù arákùnrin Olúwa.
20. Nǹkan tí èmi ń kọ̀wé sí yín yìí kíyèsí i, níwájú Ọlọ́run èmi kò ṣèké.