Ékísódù 28:15-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. “Ìwọ yóò fi iṣẹ́ ọgbọ́n ṣe ìgbàyà fún ìpinu iṣẹ́ ọnà gbẹ́nàgbẹ́nà. Ìwọ yóò ṣe é bí ẹ̀wù èfòdì ti wúrà, ti aṣọ aláró, ti elésèé àlùkò, ti òdòdó àti ti ọ̀gbọ̀ olókùn wíwẹ́ dáradára.

16. Kí ìhà mẹ́rẹ̀ẹ̀rin rẹ̀ se déédé—kí ó jẹ́ ìwọ̀n ṣẹ́ńtímítà méjìlélógún ní gíga àti ìwọ̀n ṣẹ̀ńtímítà méjìlélógun (22 centimeters) ní fífẹ̀ kí o sì ṣe é ní ìsẹ́po méjì.

17. Nígbà náà ni ìwọ yóò de òkúta iyebíye mẹ́rin sára ẹṣẹ̀ rẹ̀. Ní ẹṣẹ̀ àkọ́kọ́ ni kí rúbì, tópásì àti bérílì wà;

18. ní ẹṣẹ̀ kejì émérálídì, sáfírù, àti díámóńdì;

19. ní ẹṣẹ̀ kẹta, lígúrè, ágátè, àti ámétísítì;

20. ní ẹṣẹ̀ kẹrin, bérílù, àti óníkísì àti Jásípérì. A ó sì tò wọ́n sí ojú wúrà ní dìde wọn.

21. Òkúta méjìlá (12) yóò wà, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún orúkọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì olúkúlùkù èdìdì àmì pẹ̀lú orúkọ ẹnìkọ̀ọ̀kan bí ẹ̀yà Ísírẹ́lì méjìlá.

22. “Fún ìgbàyà náà, ìwọ yóò se okùn ẹ̀wọ̀n ti kìkì wúrà, gẹ́gẹ́ bí ọ̀já àmùrè.

23. Ìwọ yóò ṣe òrùka wúrà méjì fún un, kí o sì so wọ́n mọ́ igun igbá àyà méjèèjì.

24. Ìwọ yóò so ẹ̀wọ̀n wúrà méjèèjì mọ́ òrùka ní igun ìgbàyà náà,

Ékísódù 28