Ékísódù 21:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “Wọ̀nyí ni àwọn òfin tí ìwọ yóò gbé sí iwájú wọn:

2. “Bí ìwọ bá yá ọkùnrin Hébérù ní ìwẹ̀fà, òun yóò sìn ọ́ fún ọdún Mẹ́fà. Ṣùgbọ́n ní ọdún keje, òun yóò lọ ni òmìnira láìsan ohunkóhun padà.

3. Bí ó bá wá ní òun nìkan òun nìkan náà ni yóò padà lọ ní òmìnira; ṣùgbọ́n tí ó bá mú ìyàwó wá, ó ní láti mú ìyàwó rẹ̀ padà lọ.

4. Bí olówó rẹ̀ bá fún un ní aya, tí aya náà sì bímọ ọkùnrin àti obìnrin, aya àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò jẹ́ ti olówó rẹ̀, yóò sì lọ ní òmìnira ní òun nìkan.

5. “Bí ìwọ̀fà náà bá sọ gbangba pé, mo fẹ́ràn olówó mi, ìyàwó mi àti àwọn mi èmi kò sì fẹ́ ẹ́ gba òmíràn mọ́:

Ékísódù 21