Dáníẹ́lì 11:38-45 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

38. Ṣùgbọ́n dípò wọn, yóò bu ọlá fún òrìṣà àwọn ìlú olódi: òrìṣà tí àwọn baba rẹ̀ kò mọ̀ ni yóò bu ọlá fún pẹ̀lú wúrà àti fàdákà, pẹ̀lú òkúta iyebíye àti ẹ̀bùn tí ó lówó lórí.

39. Yóò kọ lu àwọn ìlú olódi tí ó lágbára pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ òrìṣà àjèjì, yóò sì bu ọlá ńlá fún ẹni tí ó jẹ́wọ́ rẹ̀. Yóò mú wọn ṣe alákòóso lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, yóò sì pín ilẹ̀ náà fún wọn gẹ́gẹ́ bí èrè.

40. “Ní ìgbà ìkẹyìn, ọba Gúṣù yóò gbé ogun de sí i, ọba àríwá yóò sì jáde bí ìjì láti kọ lù ú pẹ̀lú u kẹ̀kẹ́ ogun àti ẹlẹ́ṣin àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọkọ̀ ojú omi. Yóò gbógun wọ orílẹ̀ èdè púpọ̀, yóò sì gbá wọn mọ́lẹ̀ bí ìkún omi.

41. Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì tún gbógun ti ilẹ̀ ológo náà pẹ̀lú, ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀ èdè yóò ṣubú, ṣùgbọ́n Édómù, Móábù àti àwọn olórí Ámónì yóò bọ́ lọ́wọ́ ọ rẹ̀.

42. Yóò lo agbára rẹ̀ lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀ èdè; Éjíbítì kì yóò là.

43. Yóò gba àkóso ìṣúra wúrà àti fàdákà àti gbogbo orò Éjíbítì, pẹ̀lú ti Líbíyà àti Núbíà nígbà tí ó mú wọn tẹríba.

44. Ṣùgbọ́n ìròyìn láti ìlà oòrùn àti láti ìwọ̀ oòrùn yóò mú ìdáríjì bá a, yóò sì fi ìbínú ńlá jáde lọ láti parun, àti láti pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ run pátapáta.

45. Yóò sì pàgọ́ ọ rẹ̀ láàrin òkun kọjú sí àárin òkè mímọ́ ológo Síbẹ̀ yóò wá sí òpin rẹ̀, ẹnìkan kò ní ràn-án lọ́wọ́.

Dáníẹ́lì 11