Àìsáyà 29:18-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Ní ọjọ́ náà adití yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ìwé kíká náà,láti inú fìrífìrí àti òkùnkùnni àwọn ojú afọ́jú yóò ríran.

19. Lẹ́ẹ̀kan síi àwọn onírẹ̀lẹ̀ yóò yọ̀ nínú Olúwa:àwọn aláìní yóò yọ̀ nínú Ẹni Mímọ́ ti Ísírẹ́lì.

20. Aláìláàánú yóò pòórá,àwọn tí ń ṣẹlẹ́yà yóò dàwátì,gbogbo àwọn tí ó ní ojú ibi ni a ó ké lulẹ̀—

21. àwọn tí wọ́n fi ọ̀rọ̀ kan mú ẹnìkan di ẹlẹ́bi,ẹni tí ń dẹkùn mú olùgbèjà ní kóòtùtí ẹ fi ẹ̀rí èkè dun aláìṣẹ̀ ní ìdájọ́.

Àìsáyà 29