Àìsáyà 26:2-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Ṣí àwọn ìlẹ̀kùnkí àwọn olódodo orílẹ̀ èdè kí ó lè wọlé,orílẹ̀ èdè tí ó pa ìgbàgbọ́ mọ́.

3. Ìwọ yóò paámọ́ ní àlàáfíà pípéọkàn ẹni tí ó dúró ṣinṣin,nítorí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.

4. Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa títí láé,nítorí Olúwa, Olúwa ni àpátaayérayé náà.

5. Ó sọ àwọn tí ó ń gbé ní òkè di onírẹ̀lẹ̀ó rẹ ìlú agbéraga náà nílẹ̀;ó sọ ọ́ di ilẹ̀ pẹrẹṣẹó sì sọ ọ́ sílẹ̀ nínú erùpẹ̀.

6. Ẹṣẹ̀ tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ẹṣẹ̀ aninilára n nì,ipaṣẹ̀ àwọn òtòsì.

7. Ipa ọ̀nà àwọn olódodo tẹ́júÌwọ adúró ṣinṣin, ìwọ mú ọ̀nààwọn olódodo kúnná.

8. Bẹ́ẹ̀ ni, Olúwa, rírìn ní ọ̀nà òfin rẹàwa dúró dè ọ́;orúkọọ rẹ àti òkìkíì rẹàwọn ni ohun tí ọkàn wa ń fẹ́.

9. Ọkàn mi ń pòùngbẹẹ̀ rẹ ní ọ̀gànjọ́ òru;ní òwúrọ̀ ni ẹ̀mí mi ń ṣàfẹ́rí rẹ.Nígbà tí ìdájọ́ọ̀ rẹ bá sọ̀kalẹ̀ sórí ayéàwọn ènìyàn yóò kọ́ ìṣòdodo.

10. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a fi oore-ọ̀fẹ́ hàn sí àwọn ìkàwọn kò kọ́ láti ṣòdodo;kódà ní ilẹ̀ àwọn tí ó dúró ṣinṣin wọ́ntẹ̀ṣíwájú láti máa ṣe ibiwọn kò sì ka ọlá ńlá Olúwa sí.

Àìsáyà 26