2 Sámúẹ́lì 16:2-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Ọba sì wí fún Ṣíbà pé, “Kí ni wọ̀nyí?”Ṣíbà sì wí pé, “Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ̀nyí ni fún àwọn ará ilé ọba láti máa gùn àti àkàrà yìí, àti èso ẹ̀rún yìí ni fún àwọn ọdọmọdékùnrin láti jẹ; àti ọtí-wáìnì yìí ni fún àwọn aláàárẹ̀ ní ijù láti mu.”

3. Ọba sì wí pé, “Ọmọ olúwa rẹ dà?”Ṣíbà sì wí fún ọba pé, “Wò ó, ó jókòó ní Jérúsálẹ́mù; nítorí tí ó wí pé, ‘Lónìí ni ìdílé Ísírẹ́lì yóò mú ìjọba baba mi padà wá fún mi.’ ”

4. Ọba sì wí fún Síbà pé, “Wò ó, gbogbo nǹkan tí í ṣe ti Mefíbóṣétì jẹ́ tìrẹ.”Ṣíbà sì wí pé, “Mo túúbá, jẹ́ kí n rí ore-ọ̀fẹ́ lójú rẹ, Olúwa mi ọba.”

5. Dáfídì ọba sì dé Bahúrímù, sì wò ó, Ọkùnrin kan ti ibẹ̀ jáde wá, láti ìdílé Ṣọ́ọ̀lù wá, orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Ṣíméhì, ọmọ Gérà: ó sì ń bú èébú bí o tí ń bọ̀.

6. Ó sì sọ òkúta sí Dáfídì, àti sí gbogbo àwọn ènìyàn, gbogbo àwọn alágbára ọkùnrin sì wà lọ́wọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti lọ́wọ́ òsì rẹ̀.

2 Sámúẹ́lì 16