2 Ọba 17:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ọdún kejìlá ọba Áhásì ará Júdà, Hóséà ọmọ Élà jẹ ọba Ísírẹ́lì ní Ṣamáríà, ó sì jẹ fún ọdún mẹsàn án.

2. Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí i ti ọba Ísírẹ́lì ẹni tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀.

3. Ṣálámánesérì ọba Áṣíríà wá sókè láti mú Hóséà, ẹni tí ó ti jẹ fún Ṣálámánésérì ó sì ti san owó òde fún un.

4. Ṣùgbọ́n ọba Ásíríà ríi wí pé Hóséà jẹ́ ọlọ́tẹ̀, nítorí ó ti rán ońsẹ́ sọ́dọ̀ ọba Éjíbítì, kò sì san owó òde mọ́ fún ọba Áṣíríà, gẹ́gẹ́ bí o ti máa ń ṣe ní ọdọdún. Nígbà náà ọba Áṣírìa fi agbára mú-ún, ó sì fi sínú túbú.

5. Ọba Ásíríà gòkè wá sí gbogbo ibi ilé náà, ó sì lọ sí Samáríà, ó sì dúró tìí fún ọdún mẹ́ta.

2 Ọba 17