1. Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú Jehóáhásì ọmọ Jósíà wọn sì fi jẹ ọba ní Jérúsálẹ́mù ni ipọ̀ Baba rẹ̀.
2. Jehóáhásì sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́talélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ni Jérúsálẹ́mù fún ọdún mẹ́ta.
3. Ọba Éjíbítì lé e kúrò lórí ìtẹ́ ní Jérúsálẹ́mù ó sì bù fún un lórí Júdà, ọgọ́rún talẹ́ńtì fàdákà (100) àti talẹ́ntì wúrà kan.