9. Láti pèsè ọ̀pọ̀ igi rírẹ́ fún mi, nitorí ilé Olúwa tí mo kọ́ gbọdọ̀ tóbi kí o sì lógo púpọ̀.
10. Èmi yóò fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ọkùnrin onígi tí ó ń gé rírẹ́ náà ni ẹgbẹ̀rún kórísì (1,000), àlìkámà ilẹ̀ àti ẹgbẹ̀rún lọ́nà ogún (20,000) kórísì ti bálì; ẹgbẹ́rùn lọ́nà (20,000) ogún ìwẹ̀ ọtí wáìnì àti ẹgbẹ̀rún lọ́nà ogún ìwẹ̀ òróró Ólífì.”
11. Hírámù ọba Tírè fèsì padà nípasẹ̀ ìwé sí Sólómónì:“Nítorí tí Olúwa fẹ́ràn àwọn ènìyàn rẹ̀, ó ti se ọ́ ní ọba wọn.”
12. Hírámì fi kún un pe:“Ìyìn ni fún Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì, tí ó dá ọ̀run òun ayé! O ti fún ọba Dáfídì ní ọmọ tí ó gbọ́n, tí ó kún fún ìmọ̀ àti àkíyèsí, tí yóò kọ́ ilé fún Olúwa àti ààfin fún ara rẹ̀.
13. “Èmi ń rán Húrámì-Abi, sí ọ ọkùnrin tí ó kún fún ìmọ̀ ńlá,