1 Tímótíù 6:15-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Èyí ti yóò fi hàn ní ìgbà tirẹ̀, Ẹni tí í ṣe Olùbùkún àti Alágbára kan ṣoṣo náà, Ọba àwọn ọba, àti Olúwa àwọn Olúwa.

16. Ẹnìkan ṣoṣo tí ó ní àìkú, tí ń gbé inú ìmọ́lẹ̀ tí a kò lè súnmọ́, ẹni tí ènìyàn kan kò rí rí tí a kò sì lè rí: ẹni tí ọlá àti agbára títí láé ń ṣe tirẹ̀ (Àmín).

17. Kìlọ̀ fún àwọn tí ó lọ́rọ̀ ní ayé ìṣinṣinyìí kí wọn ma ṣe gbéraga, bẹ́ẹ̀ ni kí wọn má ṣe gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ àìdánilójú, bí kò se lé Ọlọ́run alààyè, tí ń fi ohun gbogbo fún wa lọ́pọ̀lọpọ̀ láti lò;

18. Kí wọn máa ṣoore, kí wọn máa pọ̀ ní iṣẹ́ rere, kí wọn múra láti pín fúnni, kí wọn ni ẹ̀mí ìbákẹ́dùn;

1 Tímótíù 6