1 Sámúẹ́lì 8:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà tí Sámúẹ́lì di arúgbó, ó yan àwọn ọmọ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí adájọ́ fún Ísírẹ́lì.

2. Orúkọ àkọ́bí rẹ̀ a máa jẹ́ Jóẹ́lì àti orúkọ ẹ̀kejì a máa jẹ́ Ábíjà, wọ́n ṣe ìdájọ́ ní Bíáṣébà.

3. Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ rẹ̀, kò rìn ní ọ̀nà rẹ̀. Wọ́n yípadà sí èrè àìṣòótọ́, wọ́n gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀, wọ́n sì ń yí ìdájọ́ po.

4. Bẹ́ẹ̀ ni, gbogbo àwọn àgbààgbà ti Ísírẹ́lì péjọ pọ̀, wọ́n sì wá sọ́dọ̀ Sámúẹ́lì ní Rámà.

5. Wọ́n wí fún un pé, “Ìwọ ti di arúgbó, àwọn ọmọ rẹ kò sì rìn ní ọ̀nà rẹ: Nísinsìn yìí, yan ọba fún wa kí or lè máa darí wa gẹ́gẹ́ bí i tí gbogbo orílẹ̀ èdè”

1 Sámúẹ́lì 8