1 Sámúẹ́lì 31:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Àwọn Fílístínì sì bá Ísírẹ́lì jà: àwọn ọkùnrin Ísírẹlì sì sá níwájú àwọn Fílístínì, àwọn tí ó fi ara pa sì ṣubú ní òkè Gílíbóà.

2. Àwọn Fílístínì sì ń lépa Ṣọ́ọ̀lù àti àwọn ọmọ rẹ̀ kíkan; àwọn Fílístínì sì pa Jónátanì àti Ábínádábù, àti Mélíkísúà, àwọn ọmọ Ṣọ́ọ̀lù.

3. Ìjà náà sì burú fún Ṣọ́ọ̀lù gidigidi, àwọn tafàtafà si ta á ní ọfà, o sì fi ara pa púpọ̀ lọ́wọ́ àwọn tafàtafà.

1 Sámúẹ́lì 31