10. A ó fọ àwọn ọ̀tá Olúwa túútúú;láti ọrun wá ni yóò sánààrá sí wọn; Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ òpin ayé.“Yóò fi agbára fún ọba rẹ̀,yóò si gbé ìwo ẹni-àmì-òróró rẹ̀ sókè.”
11. Elikánà sì lọ sí Rámà sí ilé rẹ̀, Ọmọ náà sì ń ṣe ìráńṣẹ́ fún Olúwa níwájú Élì àlùfáà.
12. Àwọn ọmọ Élì sì jẹ́ ọmọ Bélíálì; wọn kò mọ Olúwa.
13. Iṣẹ́ àwọn àlùfáà pẹ̀lú àwọn ènìyàn ni pé nígbà tí ẹnìkan bá ṣe ìrúbọ, ìráńṣẹ́ àlùfáà á dé, nígbà tí ẹran náà bá ń hó lórí iná, pẹ̀lú ọ̀pá-ẹran náà oníga mẹ́ta ní ọwọ́ rẹ̀.
14. Òun a sì fi gún inú apẹ, tàbí Kẹ́tìlì tàbí òdù, tàbí ìkòkò, gbogbo èyí tí ọ̀pá-ẹran oníga náà bá mú wá sí òkè, àlùfáà á mú un fún ara rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń ṣe sí gbogbo Ísírẹ́lì tí ó wá sí ibẹ̀ ní Ṣílò.