1 Ọba 14:14-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. “Olúwa yóò gbé ọba kan dìde fún ra rẹ̀ lórí Ísírẹ́lì tí yóò ké ilé Jéróbóámù kúrò. Ọjọ́ náà nìyìí! Kí ni? Àní nísinsìnyìí.

15. Olúwa yóò kọlu Ísírẹ́lì, yóò sì dà bí a ti ń mi ìyẹ́ nínú omi. Yóò sì fa Ísírẹ́lì tu kúrò ní ilẹ̀ rere yìí, tí ó ti fi fún àwọn baba wọn, yóò sì fọ́n wọn ká kọjá odò, nítorí wọ́n ti rú ìbínú Olúwa nípa ṣíṣe ère òrìṣà.

16. Yóò sì kọ Ísírẹ́lì sílẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí Jéróbóámù ti ṣẹ̀ àti tí ó mú Ísírẹ́lì ṣẹ̀.”

17. Nígbà náà ni aya Jéróbóámù sì dìde, ó sì lọ, ó sì lọ sí Tírà. Bí ó sì ti fi ẹsẹ̀ tẹ ìloro ilé, ọmọdé náà sì kú.

18. Wọ́n sì sin ín, gbogbo Ísírẹ́lì sì ṣọ̀fọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí láti ẹnu ìránṣẹ́ rẹ̀, Ábíjà wòlíì.

19. Ìyòókù ìṣe Jéróbóámù, bí ó ti jagun, àti bí ó ti jọba, ni a kọ sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Ísírẹ́lì.

20. Jéróbóámù sì jọba fún ọdún méjìlélógún, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Nádábù ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀.

1 Ọba 14