1 Kọ́ríńtì 3:2-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Wàrà ni mo ti fi bọ́ yín, kì í ṣe oúnjẹ; nítorí ẹ kò í tí le gbà á nísinsin yìí náà, ẹ kò í tí le gbà a.

3. Nítorí ẹ̀yin jẹ́ ti ara síbẹ̀. Nítorí, níwọ̀n bí owú jíjẹ àti ìjà sì wà láàrin ara yín, ẹ̀yin kò ha ṣe ti ayé bí? Ẹ̀yin kò ha ṣe bí ènìyàn lásán bí?

4. Ǹjẹ́ ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn lásán bí? Níwọ̀n ìgbà tí ẹ ba ń sọ pé, “Èmi ń tẹ̀lé Pọ́ọ̀lù,” àti ti ẹlòmíràn tún wí pé, “Èmi ń tẹ̀lé Àpólò.”

5. Jú gbogbo rẹ̀ lọ, kí ni Àpólò ha jẹ́, kí ni Pọ́ọ̀lù sì jẹ́, àwọn ìránṣẹ́ lásán, nípaṣẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin gbàgbọ́, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti fi fún olukúlúkù.

6. Èmi gbìn, Àpólò ń bomirin; ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni ń mú ìbísí wá.

7. Ǹjẹ́ kì í ṣe ẹni tí ó ń gbìn nǹkan kan, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe ẹni tí ń bomirin; bí kò ṣe Ọlọ́run tí ó ń mú ìbísí wá.

1 Kọ́ríńtì 3