Orin Dafidi 79:4-7 BIBELI MIMỌ (BM)

4. A ti di ẹni ẹ̀gàn lójú àwọn aládùúgbò wa;àwọn tí ó yí wa ká ń fi wá ṣe yẹ̀yẹ́;wọ́n sì ń fi wá rẹ́rìn-ín.

5. Yóo ti pẹ́ tó, OLUWA?Ṣé títí ayé ni o óo máa bínú ni?Àbí owú rẹ yóo máa jó bí iná?

6. Tú ibinu rẹ sórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò mọ̀ ọ́,ati orí àwọn ìjọba tí kò sìn ọ́.

7. Nítorí pé wọ́n ti jẹ Jakọbu run;wọ́n sì ti sọ ibùgbé rẹ di ahoro.

Orin Dafidi 79