Orin Dafidi 71:16-20 BIBELI MIMỌ (BM)

16. N óo wá ninu agbára OLUWA Ọlọrun,n óo máa kéde iṣẹ́ òdodo rẹ, àní, iṣẹ́ òdodo tìrẹ nìkan.

17. Ọlọrun, láti ìgbà èwe mi ni o ti kọ́ mi,títí di òní ni mo sì ń polongo iṣẹ́ ìyanu rẹ,

18. Nisinsinyii tí mo ti dàgbà, tí ewú sì ti gba orí mi,Ọlọrun, má kọ̀ mí sílẹ̀,títí tí n óo fi ròyìn iṣẹ́ ńlá rẹ,àní, iṣẹ́ agbára rẹ, fún gbogbo àwọn ìran tí ń bọ̀.

19. Ọlọrun, iṣẹ́ òdodo rẹ kan ojú ọ̀run,ìwọ tí o ṣe nǹkan ńlá,Ọlọrun, ta ni ó dàbí rẹ?

20. O ti jẹ́ kí n rí ọpọlọpọ ìpọ́njú ńlá,ṣugbọn óo tún mú ìgbé ayé mi pada bọ̀ sípò;óo tún ti gbé mi dìde láti inú isà òkú.

Orin Dafidi 71