Orin Dafidi 68:1-5 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Kí Ọlọrun dìde, kí àwọn ọ̀tá rẹ tú ká.Kí àwọn tí ó kórìíra rẹ̀ sá níwájú rẹ̀.

2. Bí èéfín tií pòórá,bẹ́ẹ̀ ni kí wọn parẹ́;bí ìda tií yọ́ níwájú iná,bẹ́ẹ̀ ni kí àwọn eniyan burúkú parun níwájú Ọlọrun.

3. Ṣugbọn kí inú àwọn olódodo máa dùn,kí wọn máa yọ̀ níwájú Ọlọrun;kí wọn máa yọ̀ ṣẹ̀ṣẹ̀.

4. Ẹ kọrin sí Ọlọrun, ẹ kọ orin ìyìn sí orúkọ rẹ̀,ẹ pòkìkí ẹni tí ń gun ìkùukùu lẹ́ṣin.OLUWA ni orúkọ rẹ̀;ẹ máa yọ̀ níwájú rẹ̀.

5. Baba àwọn aláìníbaba ati olùgbèjà àwọn opó ni Ọlọrun,ní ibùgbé rẹ̀ mímọ́.

Orin Dafidi 68