Orin Dafidi 31:13-17 BIBELI MIMỌ (BM)

13. Mò ń gbọ́ tí ọ̀pọ̀ eniyan ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́,bí wọ́n ti ń gbìmọ̀ pọ̀ nípa mi,tí wọ́n sì ń pète ati pa mí;wọ́n ń ṣẹ̀rù bà mí lọ́tùn-ún lósì.

14. Ṣugbọn, mo gbẹ́kẹ̀lé ọ, OLUWA,Mo ní, “Ìwọ ni Ọlọrun mi.”

15. Ìgbà mi ń bẹ ní ọwọ́ rẹ;gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi,ati lọ́wọ́ àwọn tí ń lépa mi.

16. Jẹ́ kí èmi iranṣẹ rẹ rí ojurere rẹ,gbà mí là, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀.

17. Má jẹ́ kí ojú tì mí, OLUWA,nítorí ìwọ ni mò ń ké pè.Jẹ́ kí ojú ti àwọn eniyan burúkú;jẹ́ kí ẹnu wọn wọ wòwò títí wọ ibojì.

Orin Dafidi 31