Aisaya 31:5-8 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Bí àwọn ẹyẹ tií da ìyẹ́ bo ìtẹ́ wọn,bẹ́ẹ̀ ni OLUWA àwọn ọmọ ogunyóo dáàbò bo Jerusalẹmu,yóo dáàbò bò ó, yóo sì gbà á sílẹ̀yóo dá a sí, yóo sì yọ ọ́ kúrò ninu ewu.”

6. Ẹ̀yin ọmọ Israẹli,ẹ pada sọ́dọ̀ ẹni tí ẹ ti ṣàìgbọràn sí lọpọlọpọ.

7. Nítorí pé ní ọjọ́ náà, olukuluku yóo gbé àwọn ère fadakaati ère wúrà tí ó fi ọwọ́ rẹ̀ ṣe sọnù,àwọn ère tí ó mú wọn dẹ́ṣẹ̀.

8. Idà ni yóo pa Asiria, ṣugbọn kì í ṣe láti ọwọ́ eniyan;idà tí kò ní ọwọ́ eniyan ninu ni yóo pa á run.Yóo sá lójú ogun,a óo sì kó àwọn ọmọkunrin rẹ̀ lọ máa ṣiṣẹ́ tipátipá.

Aisaya 31