Sáàmù 97:5-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Òkè gíga yọ́ gẹ́gẹ́ bí ìda níwájú Olúwa,níwájú Olúwa gbogbo ayé.

6. Àwọn ọ̀run ròyìn òdodo Rẹ̀, gbogbo ènìyàn sì rí ògo Rẹ̀.

7. Gbogbo àwọn tí ń sin òrìṣà ni ojú yóò ti,àwọn ti n fi ère ṣe àfẹ́rí ara wọnẸsìn ín, ẹ̀yin òrìṣà;

8. Síónì gbọ́, inú Rẹ̀ sì dùnìnú àwọn ilé Júdà sì dùnNítorí ìdájọ́ Rẹ, Olúwa

9. Nítorí pé ìwọ, Olúwa, ní ó ga ju gbogbo ayé lọìwọ ni ó ga ju gbogbo òrìsà lọ.

10. Jẹ kí gbogbo àwọn tí ó fẹ́ Olúwa, kórira ibi, ó pa ọkan àwọn ènìyàn mímọ́ Rẹ̀ mọ́ó gbà wọ́n ní ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú.

11. Ìmọ́lẹ̀ tàn sórí àwọn olódodoàti ayọ̀ nínú àlàyé ọkàn

12. Ẹ yọ̀ nínú Olúwa, ẹ̀yin tí ẹ jẹ́ olódodo,kí ẹ sì yin orúkọ Rẹ̀ mímọ́.

Sáàmù 97