5. Ó gbé ẹ̀rí kalẹ̀ ní Jákọ́bùo sì fìdí àṣẹ múlẹ̀ ní Ísírẹ́lì,èyí tí ó páláṣẹ fún àwọn baba ńlá waláti kọ́ àwọn ọmọ wọn,
6. Nítorí náà àwọn ìran tí ń bọ̀ yóò mọ̀ wọ́nbẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ tí a kò tí i bítí yóò dìde ti wọn yóò sọ fún àwọn ọmọ wọn
7. Nígbà náà ni wọn o fi ìgbẹ̀kẹ̀lé wọn sínú Ọlọ́runwọn kò sì ní gbàgbé iṣẹ́ Ọlọ́runṣùgbọ́n wọn o pa àṣẹ Rẹ̀ mọ́.
8. Wọn ò ní dàbí àwọn baba ńlá wọnìran aláyà líle àti ọlọ́tẹ̀tí ọkàn wọn kò sòòtọ̀ si oloore.
9. Àwọn ọkùnrin Éfúráímù, tí ó há mọ́ ọ tí wọ́n mú ọrun,wọ́n yípadà ní ọjọ́ ogun
10. Wọ́n kò pa májẹ̀mú Ọlọ́run mọ́wọn sì kọ̀ láti máa gbé nínú òfin Rẹ̀
11. Wọ́n gbàgbé ohun tí ó ti ṣe,àwọn ìyanu tí ó ti fi hàn wọ́n.
12. O ṣe ìyanu níwájú àwọn baba wọn ní ilẹ̀ Éjíbítì, ní agbégbé Síónì
13. O pín òkun níyà, ó sì mú wọn kọjáó mù kí ó nà dúró bá ebè
14. Ní ọ̀ṣán ó fi ìkúùku àwọsánmọ̀ ṣe amọ̀nà wọnàti ní gbogbo òru pẹ̀lú, ìmọ̀lẹ̀ ìná.
15. Ó sán àpáta ní ihàó si fún wọn ní omi mímu lọ́pọ̀lọpọ̀bí ẹni pé láti inú ibú wá.