Sáàmù 35:4-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Kí wọn kí ó dààmú, kí a sì ti àwọn tí ń lépa ọkàn mi lójú:kí a sì mú wọn padà,kí a sì dààmú àwọn tí ń gbérò ìpalára mi.

5. Jẹ́ kí wọn dà bí ìyàngbò níwájú afẹ́fẹ́,kí ángẹ́lì Olúwakí ó máa lé wọn kiri.

6. Jẹ́ kí ọ̀nà wọn kí ó sókùnkùnkí ó sì máa yọ́,kí áńgẹ́lì Olúwakí ó máa lépa wọn!

7. Nítorí pé, ní àìnídìí ní wọ́n dẹàwọ̀n wọn sílẹ̀ fún mi,ní àìnídìí ni wọ́n wa kòtòfún ọkàn mi.

8. Jẹ́ kí ìparun kí ó wá síorí wọn lójijì.Àwọ̀n Rẹ̀ tí ó dẹ pamọ́,kí ó mú àwọn tìkálára wọn;kí wọn ṣubú sínú kòtòsí ìparun ara Rẹ̀.

9. Nígbà náà ni ọkàn miyóò yọ̀ nínú Olúwa,àní ayọ̀ ńlá nínú ìgbàlà Rẹ̀.

10. Gbogbo egúngún mi yóò wí pé,“ìwọ Olúwa,ta ni ó dà bí i Rẹ̀?O gba talákà làlọ́wọ́ àwọn tí ó lágbárajù wọ́n lọ,talákà àti aláìnílọ́wọ́ ẹni tí ń fi ṣe ìkógun?”

11. Àwọn ẹlẹ́rìí èké dìde;wọ́n bi mi léèrè àwọn ohuntí èmi kò mọ̀.

Sáàmù 35