Sáàmù 148:5-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Ẹ jẹ́ kí wọn kí ó yin orúkọ Olúwanítorí ó pàṣẹ a sì dá wọn

6. Ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láé àti láéláéó sì ti ṣe ìlànà kan tí kì yóò já.

7. Ẹ yin Olúwa láti ilẹ̀ ayé wáẹ̀yin ẹ̀dá inú òkun títóbiàti ẹ̀yin ibú òkun

8. Mọ̀nàmọ́ná àti òjò yìnyínìdí omi àti àwọn ìkùùku,ìjì líle tí ń mú ọ̀rọ̀ Rẹ̀ ṣẹ;

9. Òkè ńlá àti gbogbo òkè kékèké,igi eléso àti gbogbo igi kédárì,

10. Àwọn ẹranko ńlá àti ẹran ọ̀sìngbogbo ohun afàyàfà àti àwọn ẹyẹ abìyẹ́:

11. Àwọn ọba ayé àti ènìyàn áye gbogboàwọn ọmọ aládé àti gbogbo àwọn onídájọ́ ayé,

Sáàmù 148