Sáàmù 139:15-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Ẹ̀dá ara mi kò pamọ́ kúrò lọdọ̀ Rẹ,nígbà tí á dá mi ní ìkọ̀kọ̀,tí a sì ń ṣiṣẹ́ ní àràbarà níìhà ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé.

16. Ojú Rẹ̀ ti rí ohun ara mi tí ó wà láìpé:àti nínú ìwé Rẹ ni a ti kọ gbogbo wọn sí,ní ojojumọ́ ni a ń dá wọn,nígbà tí ọ̀kan wọn kò tí i sí.

17. Ọlọ́run, ìrò inú Rẹ tí ṣe iyebíye tó fún mi,iye wọn ti pọ̀ tó!

18. Èmi ibá kà wọ́n, wọ́n jù iyanrin lọ ní iye:nígbà tí mo bá jí, èmi yóò wà lọ́dọ̀ Rẹ̀ ṣíbẹ̀

19. Ọlọ́run ibá jẹ pa àwọn ènìyàn búburú ní tòótọ́;nítorí náà kúrò lọ́dọ̀ mi ẹ̀yin ọkùnrin ẹ̀jẹ̀.

20. Ẹni tí ń fi inú búburú sọ̀rọ̀ sí ọ,àwọn ọ̀tá Rẹ ń pe orúkọ Rẹ ní aṣán!

Sáàmù 139