Sáàmù 135:7-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Ó mú ìkuku góke láti òpin ilẹ̀ wá:ó dá mọ̀nàmọ́ná fún òjo:ó ń mú afẹ́fé ti inú ilẹ̀ ìṣúra Rẹ̀ wá.

8. Ẹni tí ó kọlu àwọn àkọ́bí Éjíbítì,àti tí ènìyàn àti ti ẹranko.

9. Ẹni tí ó rán àmì àti iṣẹ ìyanu sí àrin Rẹ̀,ìwọ Éjíbítì, sí ara Fáráò,àti sí ara àwọn ìránṣẹ́ Rẹ̀ gbogbo.

10. Ẹni tí ó kọlu àwọn orílẹ̀ èdè púpọ̀,tí ó sì pa àwọn alágbára ọba.

11. Síónì, ọba àwọn ará Ámorì, àti Ógù,ọba Báṣánì, àti gbogbo ìjọba Kénánì:

12. Ó sì fi ilẹ̀ wọn fúnni ní ìní,ìní fún Ísírẹ́lì, ènìyàn Rẹ̀.

13. Olúwa orúkọ Rẹ dúró láéláé;ìrántí Rẹ Olúwa, láti ìran-díran.

14. Nítorí tí Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn Rẹ̀,yóò sì ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ Rẹ̀.

15. Sílífà Òun wúrà ní èrè àwọn aláìkọlà,iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn.

16. Wọn ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọ́n kò sọ̀rọ;wọn ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.

17. Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́ràn;bẹ́ẹ̀ ni kò si èèmí kan ní ẹnu wọn

Sáàmù 135