Sáàmù 119:158-169 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

158. Èmi wọ̀ àwọn ẹlẹ́tàn, inú mi sì bàjẹ́nítorí wọn kò gba ọ̀rọ̀ Rẹ gbọ́.

159. Wo bí èmi ṣe fẹ́ràn ẹ̀kọ́ Rẹ;pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ Rẹ.

160. Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ Rẹ;gbogbo òfin òdodo Rẹ láéláé ni.

161. Àwọn alákòóso ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí,ṣùgbọ́n ọkàn mi wárìrì sí ọ̀rọ̀ Rẹ.

162. Èmi yọ̀ nínú ìpinnu Rẹbí ẹni tí ó rí ìkógun púpọ̀.

163. Èmi kórìíra mo sì gba èké ṣíṣeṣùgbọ́n mo fẹ́ràn òfin Rẹ.

164. Èmi yìn ọ́ ní ìgbà méje lójúmọ́nítorí òfin òdodo Rẹ.

165. Àlàáfíà púpọ̀ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ́ sí òfin Rẹ,kò sì si ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.

166. Èmi yóò dúró de ìgbàlà Rẹ, Olúwa,èmi yóò sì tẹ̀lé àṣẹ Rẹ.

167. Èmi gba òfin Rẹ gbọ́,nítorí mo fẹ́ràn wọn púpọ̀ púpọ̀

168. Èmi ṣe ìgbọ́ràn sí ẹ̀kọ́ Rẹ àti òfin Rẹ,nítorí ìwọ mọ gbogbo ọ̀nà mi.

169. Jẹ́ kí igbe mi wá sí iwájú Rẹ, Olúwa;fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Rẹ.

Sáàmù 119