Sáàmù 113:4-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Olúwa ga lórí gbogbo ayé,àti ògo Rẹ̀ lórí àwọn ọ̀run.

5. Ta ló dàbí Olúwa Ọlọ́run wa,tí ó gbé ní ibi gíga.

6. Tí ó Rẹ ara Rẹ̀ sílẹ̀ láti wòòun tí ó ń bẹ lọ́run, àti nínú ayé!

7. Ó gbé òtòsì dìde láti inú erùpẹ̀, àti péó gbé aláìní sókè láti inú ààtàn wá.

8. Kí ó le mú-un jókòó pẹ̀lú àwọn ọmọ aládéàní pẹ̀lú àwọn ọmọ aládé àwọn ènìyàn Rẹ̀.

9. Ó mú àgàn obìnrin gbé inú ilé,àti láti jẹ́ aláyọ̀ ìyá fún àwọn ọmọ Rẹ̀.Ẹ yin Olúwa.

Sáàmù 113