31. Jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ Rẹ̀àti iṣẹ́ ìyanu Rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.
32. Jẹ́ kí wọn gbé e ga ní àárin àwọn ènìyànkí wọn kí ó sì yín ín ní ìjọ àwọn àgbà.
33. Ó sọ odò di ihà,àti orisun omi di ilẹ̀ gbígbẹ.
34. Ilẹ̀ eleso di aṣálẹ̀ nítorí ìwà búburú àwọn tí ó wà nínú Rẹ̀;
35. O sọ ihà di adágún omi àtiilẹ̀ gbígbẹ di oríṣun omi
36. Níbẹ̀ ó mú ẹni tí ebi ń pa wà,wọ́n sì pìlẹ̀ ibi tí wọn ó máa gbé
37. Wọn fún irúgbìn, wọ́n sì gbin ọgbà àjàràtí yóò ma so èso tí ó dára;
38. Ó bùkún wọn, wọ́n sì pọ̀ sí i ní iyekò sí jẹ́ kí ẹran ọ̀sìn wọn kí ó dín kù.