Sáàmù 106:27-32 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

27. Láti jẹ́ kí àwọn ọmọ Rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀ èdèláti fọ́nu wọn káàkiri lórí ilẹ̀.

28. Wọn dá ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Péórù,wọn sì ń jẹ ẹbọ ti a rú sí àwọn òkú òrìṣà

29. Wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣeàjàkálẹ̀-àrùn jáde láàrin wọn.

30. Ṣùgbọ́n Fínéhásì dìde láti dá sí i,àjàkálẹ̀-àrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán

31. A sì ka èyí sí òdodo fún un àtifún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀

32. Níbi omi Méríbà, wọn bí Ọlọ́run nínú,ohun búburú wá sí orí Mósè nítorí wọn.

Sáàmù 106