Sáàmù 105:30-36 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

30. Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá,èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.

31. Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣnṣin sì dìde,ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn

32. Ó sọ òjò di yìnyín,àti ọ̀wọ́ iná ní ilẹ̀ wọn;

33. Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọnó sì dá igi orílẹ̀ èdè wọn.

34. Ó sọ̀rọ̀, eésú sì dé,àti kòkòrò ní àìníye,

35. Wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn,wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run

36. Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn,ààyò gbogbo ipá wọ́n.

Sáàmù 105