Sáàmù 105:13-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Wọn ń lọ láti orílẹ̀ èdè sí orílẹ̀ èdè,láti ìjọba kan sí òmìrán.

14. Kò gba ẹnikẹ́ni láàyè láti pọ́n wọn lójú;ó fi ọba bú nítorí tí wọn:

15. “Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi,má sì ṣe wòlíì mi nibi.”

16. Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náàó sì pa gbogbo ìpèṣè oúnjẹ wọn run;

17. Ó sì rán ọkùnrin kan ṣíwájú wọnJósẹ́fù tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.

18. Wọn fi sẹkẹ́sẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ Rẹ̀a gbé ọrùn Rẹ̀ sínú irin

19. Títí ọ̀rọ̀ tí ó sọ tẹ́lẹ̀ fi ṣẹtítí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.

20. Ọba ránsẹ́ lọ tú u sílẹ̀àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀

21. Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ Rẹ̀aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,

Sáàmù 105