Sáàmù 105:11-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. “Fún ìwọ ní èmi ó fún ní ilẹ̀ Kénánìgẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún”.

12. Nígbà tí wọn kéré níye,wọn kéré jọjọ, àti àwọn àjòjì níbẹ̀

13. Wọn ń lọ láti orílẹ̀ èdè sí orílẹ̀ èdè,láti ìjọba kan sí òmìrán.

14. Kò gba ẹnikẹ́ni láàyè láti pọ́n wọn lójú;ó fi ọba bú nítorí tí wọn:

15. “Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi,má sì ṣe wòlíì mi nibi.”

16. Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náàó sì pa gbogbo ìpèṣè oúnjẹ wọn run;

17. Ó sì rán ọkùnrin kan ṣíwájú wọnJósẹ́fù tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.

18. Wọn fi sẹkẹ́sẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ Rẹ̀a gbé ọrùn Rẹ̀ sínú irin

Sáàmù 105