Òwe 23:29-34 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

29. Ta ni ó ni òsì? Ta ni ó ni ìbànújẹ́?Ta ni ó ni ìjà? Ta ni ó ni aṣọ̀? Ta ni ó ni ọgbẹ́ láìnídìí?

30. Àwọn tí ó dúró pẹ́ níbi ọtí-wáìnì;àwọn tí ń lọ láti dán ọtí wáìnì àdàlú wò.

31. Ìwọ má ṣe wò ọtí-wáìnì nígbà tí ó pọ́n,nígbà tí ó bá ń fi àwọ̀ rẹ̀ hàn nínú ago,tí a gbé e mì, tí ó ń dùn.

32. Níkẹyìn òun á bunisán bí ejò,a sì bunijẹ bí i paramọ́lẹ̀.

33. Ojú rẹ yóò wò àwọn àjèjì obìnrin,àyà rẹ yóò sì sọ̀rọ àyídáyidà.

34. Nítòótọ́, ìwọ ó dàbí ẹni tí ó dùbúlẹ̀ ní àárin òkun,tàbí ẹni tí ó dúbúlẹ̀ lókè-ọkọ̀.

Òwe 23