Òwe 23:13-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Má ṣe fa ọwọ́ ìbáwí sẹ́yìn kúrò lára ọmọdé,nítorí pé bí ìwọ bá fi pàṣán nà án, òun kì yóò kú.

14. Bí ìwọ fi pàṣán nà án,ìwọ ó sì gbà ọkàn rẹ̀ là kúrò ní ọ̀run-àpáàdì.

15. Ọmọ mi, bí ọkàn rẹ bá gbọ́n,ọkàn mi yóò yọ̀, àní èmi pẹ̀lú.

16. Inú mi yóò sì dùn nígbà tí ètè rẹ̀ bá ń sọ̀rọ̀ títọ́.

17. Má ṣe jẹ́ kí àyà rẹ ó ṣe ìlara sí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,ṣùgbọ́n kí ìwọ ó wà ní ìbẹ̀rù Olúwa,ní ọjọ́ gbogbo.

Òwe 23