Òwe 16:19-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. ó sàn láti jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ ọkàn láàrin àwọn olùpọ́njújù láti máa pín ìpín pẹ̀lú àwọn agbéraga.

20. Ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé ẹ̀kọ́ yóò rí ire,ìbùkún sì ni fún ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ lé Olúwa.

21. Àwọn tí ó gbọ́n nínú ọkàn là ń pè ní olóyeọ̀rọ̀ ìtura sì ń mú ẹ̀kọ́ gbèrú.

22. Òye jẹ́ oríṣun ìyè fún àwọn tí ó ní i,ṣùgbọ́n ìwà òmùgọ̀ ń kó ìyà jẹ aláìgbọ́n.

23. Ọkàn ọlọgbọ́n ènìyàn a máa ṣọ́ ẹnu rẹ̀ètè rẹ̀ sì ń mú kí ẹ̀kọ́ gbèrú.

24. Ọ̀rọ̀ ìtura dàbí afárá oyinó dùn fún ọkàn, ó sì fi ìlera fún egungun.

25. Ọ̀nà kan tí ó dàbí i pé ó dára lójú ènìyànṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn a ṣokùnfà ikú.

Òwe 16