Òwe 15:17-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Oúnjẹ ewébẹ̀ níbi tí ìfẹ́ wàsàn ju àbọ́pa màlúù tòun ti ìríra.

18. Ènìyàn onínú ríru dá ìjà sílẹ̀ṣùgbọ́n onísùúrù paná ìjà.

19. Ẹ̀gún dí ọ̀nà ọ̀lẹṣùgbọ́n pópónà tí ń dán ni ti àwọn dídúró ṣinṣin.

20. Ọlọgbọ́n ọmọ mú inú baba rẹ̀ dùn,ṣùgbọ́n aláìgbọ́n ọmọ kẹ́gàn baba rẹ̀.

21. Inú ènìyàn aláìlóye a máa dùn sí ìwà òmùgọ̀;ṣùgbọ́n olóye ènìyàn a máa rin ọ̀nà tààrà.

22. Ìgbèrò a máa dasán níbi tí kò sí ìmọ̀ràn;ṣùgbọ́n a máa yege níbi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùbádámọ̀ràwà.

Òwe 15