Orin Sólómónì 2:3-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Bí igi ápù láàrin àwọn igi inú igbó,ni olùfẹ́ mí láàrin àwọn ọ̀dọ́mọkùnrinMo fi ayọ̀ jókòó ní abẹ́ òjìji rẹ̀,Èso rẹ̀ sì dùn mọ́ mi ní ẹnu.

4. Ó mú mi lọ sí ibi gbọ̀ngàn àṣè,Ìfẹ́ sì ni ọ̀pàgun rẹ̀ lórí mi.

5. Fi agbára adùn àkàrà dá mi dúró.Fi èṣo ápù tù mi láraNítorí àìsàn ìfẹ́ ń ṣe mí.

6. Ọwọ́ òsì rẹ ń bẹ lábẹ́ orí miỌwọ́ ọ̀tún rẹ sì ń gbà mí mọ́ra

7. Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jérúsálẹ́mù,mo fi abo egbin àti ọmọ àgbọ̀nrín fi yín búKí ẹ má ṣe ru ìfẹ́ olùfẹ́ mi sókèKí ẹ má sì ṣe jí i títí yóò fi wù ú

8. Gbọ́ ohùn olùfẹ́ mi!Wò ó! Ibí yìí ni ó ń bọ̀.Òun ń fò lórí àwọn òkè ńlá,Òun bẹ́ lórí àwọn òkè kékèké

Orin Sólómónì 2