Onídájọ́ 12:8-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Lẹ́yìn Jẹ́fítà, Íbísánì ará Bẹ́tílẹ́hẹ́mù ṣe ìdájọ́ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.

9. Ó ní ọgbọ̀n (30) ọmọkùnrin àti ọgbọ̀n ọmọbìnrin fún àwọn tí kì í ṣe ẹ̀yà rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìyàwó, ó sì fẹ́ ọgbọ̀n àwọn ọmọbìnrin fún àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin lára àwọn tí kì í ṣe ẹ̀yà rẹ̀. Ó ṣe ìdájọ́ Ísírẹ́lì fún ọdún méje.

10. Lẹ́yìn náà ni Íbísánì kú, wọ́n sì sin ín sí Bẹ́tílẹ́hẹ́mù.

11. Lẹ́yìn rẹ̀, Élónì ti ẹ̀yà Ṣébúlúnì ṣe àkóso Ísírẹ́lì fún ọdún mẹ́wàá.

Onídájọ́ 12