Nọ́ḿbà 24:11-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Nísinsìnyìí kúrò lọ́dọ̀ mi kíákíá kí o sì máa relé! Mo sọ wí pé màá sọ ọ́ di ẹni ńlá, ṣùgbọ́n Olúwa kò jẹ́ kí o gba èrè yìí.”

12. Bálámù dá Bálákì lóhùn, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí o rán sí mi wí pé,

13. ‘Kó dà bí Bálákì bá fún mi ní ààfin rẹ̀ tí ó kún fún fàdákà àti wúrà, n kò le ṣe ohunkóhun lọ́wọ́ ara mi, yálà búburú tàbí rere, láti kọjá òfin Olúwa: ohun tí Olúwa bá wí ni èmi ó sọ’?

14. Nísinsin yìí mò ń padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó kìlọ̀ fún ọ nítorí nǹkan tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò ṣe sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú.”

15. Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe:“Òwe Bálámù ọmọ Béórì,òwe ẹnì tí ojú rẹ̀ ríran kedere,

16. òwe ẹni kan tí etí rẹ̀ ń gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run,tí ó ní ọgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Ẹni gíga jùlọ,tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè,ẹni tí ó dọ̀bálẹ̀, tí ojú rẹ̀ sì sí:

17. “Mo rí i, ṣùgbọ́n kì í ṣe ìsinsin yìí,Mo kíyèsi, ṣùgbọ́n kò súnmọ́.Ìràwọ̀ kan yóò jáde láti ọ̀dọ̀ Jákọ́bù;yóò yọ jáde láti Ísírẹ́lì.Yóò tẹ̀ fọ́ orí Móábù,yóò sì fọ́ agbárí gbogbo ọmọ Ṣéétì.

18. Wọn yóò borí Édómù;yóò ṣẹ́gun Ṣéérì ọ̀ta rẹ̀,ṣùgbọ́n Ísírẹ́lì yóò dàgbà nínú agbára.

19. Olórí yóò jáde láti Jákọ́bùyóò sì pa àwọn tó ṣẹ́kù nínú ìlú náà run.”

Nọ́ḿbà 24