Nọ́ḿbà 2:2-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. “Kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pa Àgọ́ wọn yí àgọ́ ìpàdé ká, kí wọ́n jẹ́ kí àgọ́ wọn jìnnà sí i díẹ̀, oníkálùkù lábẹ́ ọ̀págun pẹ̀lú àṣíá ìdílé wọn.”

3. Ní ìlà oòrùn, ní ìdojúkọ àtiyọ oòrùn ni kí ìpín ti Júdà pa ibùdó wọn sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Júdà ni Náṣónì ọmọ Ámínádábù.

4. Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tadínlógójì ó lé ẹgbẹ̀ta (74,600).

5. Ẹ̀yà Ísákárì ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Ísákárì ni Nìtaníẹ́lì ọmọ Súárì.

6. Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tadínlọ́gbọ̀n ó lé irínwó (54,400).

7. Ẹ̀yà Sébúlúnì ni yóò tẹ̀lé e. Olórí Sébúlónì ni Élíábù ọmọ Hélónì.

8. Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gbọ̀n-ó-lé-egbéje (57,400).

9. Gbogbo àwọn tí a yàn sí ibùdó Júdà, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́taléláàdọ́rin ó lé irínwó (186,400). Àwọn ni yóò kọ́kọ́ ṣáájú.

10. Ní ìhà gúsù ni ìpín ti Rúbẹ́nì pa ibùdó sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Rúbẹ́nì ni Elisúrì ọmọ Ṣedúérì.

11. Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́talélógún ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta. (46,500).

12. Ẹ̀yà Símónì ni yóò pa ibùdó tẹ́lé wọn. Olórí Símónì ni Ṣélúmíélì ọmọ Surisadáì.

13. Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbéje. (59,300).

14. Ẹ̀yà Gáádì ló tẹ̀lé wọn. Olórí Gáádì ni Eliásáfì ọmọ Déúélì.

15. Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé àádọ́ta (45,650).

16. Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Rúbẹ́nì, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá márùndínlọ́gọ́rún ó lé àádọ́tàlélégbéje (151,450). Àwọn ni yóò jáde sìkéjì.

17. Nígbà náà ni àwọn ọmọ Léfì Àti Àgọ́ ìpàdé yóò tẹ̀ṣíwájú láàrin ibùdó àwọn ènìyàn, wọn yóò tẹ̀ṣíwájú ní ṣíṣẹ̀ n tẹ̀lé gẹ́gẹ́ bí wọn ṣe pa ibùdó, olúkúlùkù láàyè rẹ̀, àti lábẹ́ ọ̀págun rẹ̀.

18. Ní ìhà ìlà oòrùn ni ìpín Éfúráímù yóò pa ibùdó rẹ̀ sí lábẹ́ ọ́págun rẹ̀. Olórí Éfúráímù ni Élíṣámà ọmọ Ámíhúdì.

Nọ́ḿbà 2