29. Àwọn Ámálékì ń gbé ní ilẹ̀ Gúsù; àwọn ará Hítì, àwọn ará Jébúsì àti àwọn ará Ámórì ni wọ́n ń gbé ní orí òkè ilẹ̀ náà, àwọn ará Kénánì sì ń gbé ẹ̀bá òkun àti ní etí bèbè Jọ́dánì.”
30. Kélẹ́bù sì pa àwọn ènìyàn náà lẹ́nu mọ́ níwájú Mósè, ó wí pé, “Ẹ jẹ́ kí á gòkè lọ lẹ́ẹ̀kan náà láti lọ gba ilẹ̀ náà, nítorí pé àwa le è gbà á.”
31. Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin tí wọ́n jọ gòkè lọ yẹ ilẹ̀ wò sọ pé, “Àwa kò le gòkè lọ bá àwọn ènìyàn wọ̀nyí nítorí pé wọ́n lágbára jù wá lọ.”
32. Báyìí ni wọ́n ṣe mú ìròyìn búburú wá nípa ilẹ̀ tí wọ́n lọ yẹ̀ wò. Wọ́n wí pé, “Ilẹ̀ tí a lọ yẹ̀ wò jẹ́ ilẹ̀ tí ń run àwọn olùgbé ibẹ̀. Gbogbo àwọn ènìyàn tí a rí níbẹ̀ jẹ́ ènìyàn tó fìrìgbọ̀n tó sì sígbọnlẹ̀.
33. A sì tún rí àwọn òmìrán (irú àwọn ọmọ Ánákì) àwa sì rí bí i kòkòrò tata ní ojú ara wa, bẹ́ẹ̀ ni àwa náà sì rí ní ojú wọn.”